Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 19:24-37 Yorùbá Bibeli (YCE)

24. Emi ti wà kànga, emi si ti mu ajèji omi, atẹlẹsẹ̀ mi li emi si ti fi gbẹ gbogbo odò Egipti.

25. Iwọ kò ti gbọ́, lailai ri emi ti ṣe e, nigba atijọ emi si ti mura tẹlẹ nisisiyi emi ti mu u ṣẹ, ki iwọ ki o le mã sọ ilu olodi wọnni di ahoro, ani di òkiti àlapa.

26. Nitorina ni awọn olugbe wọn fi ṣe alainipa, a daiyàfo wọn nwọn si dãmu; nwọn dàbi koriko igbẹ́, ati bi ewebẹ̀ tutù, bi koriko li ori ile, ati bi ọkà ti o rẹ̀ danù ki o to dàgba soke.

27. Ṣugbọn emi mọ̀ ijoko rẹ, ati ijadelọ rẹ, ati bibọ̀ rẹ, ati ikannu rẹ si mi.

28. Nitori ikánnu rẹ si mi ati irera rẹ de eti mi, nitorina li emi o fi ìwọ̀ mi kọ́ ọ ni imu, ati ijanu mi si ẹnu rẹ, emi o si yi ọ pada si ọ̀na na ti iwọ ti ba wá.

29. Eyi ni yio si ṣe àmi fun ọ, Ẹ jẹ ilalẹ̀hu li ọdun ni, ati li ọdun keji eyiti o hù ninu ọkanna; ati li ọdun kẹta ẹ fun irúgbìn, ki ẹ si kore, ki ẹ si gbìn ọgba ajara, ki ẹ si jẹ eso rẹ̀.

30. Iyokù ile Juda ti o salà yio si tún ta gbòngbo si isàlẹ, yio si so eso li òke.

31. Nitori lati Jerusalemu li awọn iyokù yio jade lọ, ati awọn ti o salà lati oke Sioni jade: itara Oluwa awọn ọmọ-ogun ni yio ṣe eyi.

32. Nitori bayi li Oluwa wi niti ọba Assiria, On kì yio wá si ilu yi, bẹ̃ni kì yio ta ọfà kan sibẹ, kì yio mu asà wá iwaju rẹ̀, bẹ̃ni kì yio mọ odi tì i yika.

33. Ọna na ti o ba wá, ọkanna ni yio ba pada lọ, kì yio si wá si ilu yi, li Oluwa wi.

34. Nitori emi o da abò bò ilu yi, lati gbà a, nitori ti emi tikara mi, ati nitori ti Dafidi iranṣẹ mi.

35. O si ṣe li oru na ni angeli Oluwa jade lọ, o si pa ọkẹ́ mẹsan le ẹgbẹ̃dọgbọn enia ni ibùbo awọn ara Assiria: nigbati nwọn si dide ni kutukutu owurọ, kiyesi i, okú ni gbogbo wọn jasi.

36. Bẹ̃ni Sennakeribu ọba Assiria mu ọ̀na rẹ̀ pọ̀n, o si lọ, o si pada, o si joko ni Ninefe.

37. O si ṣe, bi o ti mbọ̀riṣa ni ile Nisroku oriṣa rẹ̀, ni Adrammeleki ati Ṣareseri awọn ọmọ rẹ̀ fi idà pa a: nwọn si sa lọ si ilẹ Armenia. Esarhaddoni ọmọ rẹ̀ sì jọba ni ipò rẹ̀.