Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 17:34-41 Yorùbá Bibeli (YCE)

34. Titi di oni yi nwọn nṣe bi iṣe wọn atijọ: nwọn kò bẹ̀ru Oluwa, bẹ̃ni nwọn kò ṣe bi idasilẹ wọn, tabi ilàna wọn, tabi ofin ati aṣẹ ti Oluwa pa fun awọn ọmọ Jakobu, ti o sọ ni Israeli;

35. Awọn ẹniti Oluwa ti ba dá majẹmu, ti o si ti kilọ fun wọn, wipe, Ẹnyin kò gbọdọ bẹ̀ru awọn ọlọrun miran, bẹ̃ni ẹnyin kò gbọdọ tẹ̀ ara nyin ba fun wọn, tabi ki ẹ sìn wọn, tabi ki ẹ rubọ si wọn:

36. Ṣugbọn Oluwa ti o mu nyin gòke ti ilẹ Egipti wá, pẹlu agbara nla ati ninà apá, on ni ki ẹ mã bẹ̀ru, on ni ki ẹ si mã tẹriba fun, on ni ki ẹ sì mã rubọ si.

37. Ati idasilẹ wọnni, ati ilàna wọnni, ati ofin ati aṣẹ ti o ti kọ fun nyin, li ẹnyin o mã kiyesi lati mã ṣe li ọjọ gbogbo; ẹnyin kò si gbọdọ bẹ̀ru awọn ọlọrun miràn.

38. Ati majẹmu ti mo ti ba nyin dá ni ẹnyin kò gbọdọ gbàgbe; bẹ̃ni ẹnyin kò gbọdọ bẹ̀ru awọn ọlọrun miran.

39. Ṣugbọn Oluwa Ọlọrun nyin ni ẹnyin o mã bẹ̀ru; on ni yio si gbà nyin lọwọ awọn ọta nyin gbogbo.

40. Nwọn kò si gbọ́, ṣugbọn nwọn ṣe bi iṣe wọn atijọ.

41. Bẹ̃li awọn orilẹ-ède wọnyi bẹ̀ru Oluwa, ṣugbọn nwọn tun sin awọn ere fifin wọn pẹlu; awọn ọmọ wọn, ati awọn ọmọ-ọmọ wọn, bi awọn baba wọn ti ṣe, bẹ̃li awọn na nṣe titi fi di oni yi.