Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 17:28-36 Yorùbá Bibeli (YCE)

28. Nigbana ni ọkan ninu awọn alufa ti nwọn ti kó ti Samaria lọ, wá, o si joko ni Beteli, o si kọ́ wọn bi nwọn o ti mã bẹ̀ru Oluwa.

29. Ṣugbọn olukuluku orilẹ-ède ṣe oriṣa tirẹ̀, nwọn si fi wọn sinu ile ibi giga wọnni ti awọn ara Samaria ti ṣe, olukuluku orilẹ-ède ninu ilu ti nwọn ngbe.

30. Awọn enia Babeli ṣe agọ awọn wundia, ati awọn enia Kuti ṣe oriṣa Nergali, ati awọn enia Hamati ṣe ti Aṣima,

31. Ati awọn ara Afa ṣe ti Nibhasi ati ti Tartaki, ati awọn ara Sefarfaimu sun awọn ọmọ wọn ninu iná fun Adrammeleki ati Anammeleki awọn òriṣa Sefarfaimu.

32. Nwọn bẹ̀ru Oluwa pẹlu, nwọn si ṣe alufa ibi giga wọnni fun ara wọn, ninu awọn enia lasan, ti nrubọ fun wọn ni ile ibi giga wọnni.

33. Nwọn bẹ̀ru Oluwa, nwọn si nsìn oriṣa wọn gẹgẹ bi iṣe awọn orilẹ-ède, ti nwọn kó lati ibẹ lọ.

34. Titi di oni yi nwọn nṣe bi iṣe wọn atijọ: nwọn kò bẹ̀ru Oluwa, bẹ̃ni nwọn kò ṣe bi idasilẹ wọn, tabi ilàna wọn, tabi ofin ati aṣẹ ti Oluwa pa fun awọn ọmọ Jakobu, ti o sọ ni Israeli;

35. Awọn ẹniti Oluwa ti ba dá majẹmu, ti o si ti kilọ fun wọn, wipe, Ẹnyin kò gbọdọ bẹ̀ru awọn ọlọrun miran, bẹ̃ni ẹnyin kò gbọdọ tẹ̀ ara nyin ba fun wọn, tabi ki ẹ sìn wọn, tabi ki ẹ rubọ si wọn:

36. Ṣugbọn Oluwa ti o mu nyin gòke ti ilẹ Egipti wá, pẹlu agbara nla ati ninà apá, on ni ki ẹ mã bẹ̀ru, on ni ki ẹ si mã tẹriba fun, on ni ki ẹ sì mã rubọ si.