Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 19:1-4 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. O si ṣe, nigbati Hesekiah ọba gbọ́, o si fà aṣọ rẹ̀ ya, o si fi aṣọ ọ̀fọ bò ara rẹ̀, o si lọ sinu ile Oluwa.

2. O si rán Eliakimu, ti iṣe olori ile, ati Ṣebna akọwe, ati awọn àgba alufa, ti nwọn fi aṣọ ọ̀fọ bò ara, sọdọ Isaiah woli ọmọ Amosi.

3. Nwọn si wi fun u pe, Bayi ni Hesekiah wi, Ọjọ oni ọjọ wàhala ni, ati ti ibawi, ati ẹgàn: nitoriti awọn ọmọ de oju-ibí, kò si si agbara lati bi.

4. Bọya Oluwa Ọlọrun rẹ yio gbọ́ gbogbo ọ̀rọ Rabṣake ẹniti ọba Assiria oluwa rẹ̀ ti rán lati kẹgàn Ọlọrun alãyè, yio si ba a wi nitori ọ̀rọ ti Oluwa Ọlọrun rẹ ti gbọ́: njẹ nitorina, gbé adura rẹ soke fun awọn iyokù ti o kù.