Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 16:15-20 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Ahasi ọba si paṣẹ fun Urijah alufa, wipe, Lori pẹpẹ nla ni ki o mã sun ọrẹ-sisun orowurọ̀ ati ọrẹ-jijẹ alalẹ, ati ẹbọ-sisun ti ọba, ati ọrẹ-jijẹ rẹ̀, pẹlu ọrẹ-sisun ti gbogbo awọn enia ilẹ na, ati ọrẹ-jijẹ wọn, ati ọrẹ ohun-mimu wọn; ki o si wọ́n gbogbo ẹ̀jẹ ọrẹ-sisun na lori rẹ̀, ati gbogbo ẹ̀jẹ ẹbọ miran: ṣugbọn niti pẹpẹ idẹ na emi o mã gbero ohun ti emi o fi i ṣe.

16. Bayi ni Urijah alufa ṣe, gẹgẹ bi gbogbo eyiti Ahasi ọba pa li aṣẹ.

17. Ahasi ọba si ké alafo ọnà arin awọn ijoko na, o si ṣi agbada na kuro lara wọn; o si gbé agbada-nla na kalẹ kuro lara awọn malu idẹ ti mbẹ labẹ rẹ̀, o si gbé e kà ilẹ ti a fi okuta tẹ́.

18. Ibi ãbò fun ọjọ isimi ti a kọ́ ninu ile na, ati ọ̀na ijade si ode ti ọba, ni o yipada kuro ni ile Oluwa nitori ọba Assiria.

19. Ati iyokù iṣe Ahasi ti o ṣe, a kò ha kọ wọn sinu iwe ọ̀rọ ọjọ awọn ọba Juda?

20. Ahasi si sùn pẹlu awọn baba rẹ̀, a si sin i pẹlu awọn baba rẹ̀ ni ilu Dafidi: Hesekiah ọmọ rẹ̀ si jọba ni ipò rẹ̀.