Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 12:9-14 Yorùbá Bibeli (YCE)

9. Ṣugbọn Jehoiada alufa mu apoti kan, o si dá ideri rẹ̀ lu, o si fi i si ẹba pẹpẹ na, li apa ọtún bi ẹnikan ti nwọ̀ inu ile Oluwa lọ: awọn alufa ti o si ntọju iloro na fi gbogbo owo ti a mu wá inu ile Oluwa sinu rẹ̀.

10. O si ṣe, nigbati nwọn ri pe, owo pupọ̀ mbẹ ninu apoti na, ni akọwe ọba, ati olori alufa gòke wá, nwọn si dì i sinu apò, nwọn si kà iye owo ti a ri ninu ile Oluwa.

11. Nwọn si fi owo na ti a kà le ọwọ awọn ti o nṣiṣẹ na, awọn ti o nṣe abojuto ile Oluwa: nwọn si ná a fun awọn gbẹnagbẹna, ati awọn akọle, ti nṣiṣẹ ile Oluwa.

12. Ati fun awọn ọmọle, ati awọn agbẹ́kuta, ati lati rà ìti-igi ati okuta gbígbẹ lati tun ẹya ile Oluwa ṣe, ati fun gbogbo eyi ti a ná fun ile na lati tun u ṣe.

13. Ṣugbọn ninu owo ti a mu wá sinu ile Oluwa, a kò fi ṣe ọpọ́n fadakà, alumagàji fitila, awokoto, ipè ohun èlo wura tabi ohun elò fadakà kan fun ile Oluwa:

14. Ṣugbọn nwọn fi i fun awọn ti nṣiṣe na, nwọn si fi tun ile Oluwa ṣe.