Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 8:7-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

7. Eliṣa si wá si Damasku; Benhadadi ọba Siria si nṣe aisàn; a si sọ fun u, wipe, Enia Ọlọrun de ihinyi.

8. Ọba si wi fun Hasaeli pe, Mu ọrẹ lọwọ rẹ, si lọ ipade enia Ọlọrun na, ki o si bère lọwọ Oluwa lọdọ rẹ̀, wipe, Emi o ha sàn ninu arùn yi?

9. Bẹ̃ni Hasaeli lọ ipade rẹ̀, o si mu ọrẹ li ọwọ rẹ̀, ani ninu gbogbo ohun rere Damasku, ogoji ẹrù ibakasiẹ, o si de, o si duro niwaju rẹ̀, o si wipe, Ọmọ rẹ Benhadadi ọba Siria rán mi si ọ, wipe, Emi o ha sàn ninu arùn yi?

10. Eliṣa si wi fun u pe, Lọ, ki o si sọ fun u pe, Iwọ iba sàn nitõtọ: ṣugbọn Oluwa ti fi hàn mi pe, nitõtọ on o kú.

11. On si tẹ̀ oju rẹ̀ mọ ọ gidigidi, titi oju fi tì i; enia Ọlọrun na si sọkun.

12. Hasaeli si wipe, Ẽṣe ti oluwa mi fi nsọkun? On si dahùn pe, Nitoriti mo mọ̀ ibi ti iwọ o ṣe si awọn ọmọ Israeli: awọn odi agbara wọn ni iwọ o fi iná bọ̀, awọn ọdọmọkunrin wọn ni iwọ o fi idà pa, iwọ o si fọ́ ọmọ wẹwẹ́ wọn tútu, iwọ o si là inu awọn aboyun wọn.