Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 2:17-25 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. Nigbati nwọn si rọ̀ ọ titi oju fi tì i, o wi fun wọn pe, Ranṣẹ. Nitorina nwọn rán ãdọta ọkunrin, nwọn si wá a ni ijọ mẹta, ṣugbọn nwọn kò ri i.

18. Nwọn si tun pada tọ̀ ọ wá, (nitori ni Jeriko li o joko,) o wi fun wọn pe, Emi kò ti wi fun nyin pe, Ẹ máṣe lọ?

19. Awọn ọkunrin ilu na si wi fun Eliṣa pe, Kiyesi i, itẹ̀do ilu yi dara, bi oluwa mi ti ri i: ṣugbọn omi buru, ilẹ si ṣá.

20. On si wipe, Mu àwokóto titun kan fun mi wá, si fi iyọ̀ sinu rẹ̀; nwọn si mu u tọ̀ ọ wá.

21. On si jade lọ si ibi orisun omi na, o si dà iyọ na sibẹ, o si wipe, Bayi li Oluwa wi, Emi ṣe àwotan omi wọnyi; lati ihin lọ, kì yio si ikú mọ, tabi aṣálẹ.

22. Bẹ̃ni a ṣe àwotan omi na titi di oni oloni, gẹgẹ bi ọ̀rọ Eliṣa ti o sọ.

23. O si gòke lati ibẹ lọ si Beteli: bi o si ti ngòke lọ li ọ̀na, awọn ọmọ kekeke jade lati ilu wá, nwọn si nfi ṣe ẹlẹyà, nwọn si wi fun u pe, Gòke lọ, apari! gòke lọ, apari!

24. O si yipada, o si wò wọn, o si fi wọn bú li orukọ Oluwa. Abo-beari meji si jade lati inu igbó wá, nwọn si fà mejilelogoji ya ninu wọn.

25. O si ti ibẹ lọ si òke Karmeli; ati lati ibẹ o pada si Samaria.