Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 17:1-4 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. LI ọdun kejila Ahasi ọba Juda ni Hoṣea ọmọ Ela bẹ̀rẹ si ijọba ni Samaria, lori Israeli li ọdun mẹsan.

2. O si ṣe eyiti o buru li oju Oluwa, ṣugbọn kì iṣe bi awọn ọba Israeli ti o ti wà ṣãju rẹ̀.

3. On ni Ṣalamaneseri ọba Assiria gòke tọ̀ wá; Hoṣea si di iranṣẹ rẹ̀, o si ta a li ọrẹ.

4. Ọba Assiria si ri ọ̀tẹ ninu Hoṣea: nitoriti o ti rán onṣẹ sọdọ So ọba Egipti, kò si mu ọrẹ fun ọba Assiria wá bi iti mã iṣe li ọdọdun; nitorina ni ọba Assiria há a mọ, o si dè e ni ile tubu.