Yorùbá Bibeli

1. A. Ọba 8:57-62 Yorùbá Bibeli (YCE)

57. Oluwa Ọlọrun wa ki o wà pẹlu wa, bi o ti wà pẹlu awọn baba wa: ki o má fi wa silẹ, ki o má si ṣe kọ̀ wa silẹ;

58. Ṣugbọn ki o fa ọkàn wa si ọdọ ara rẹ̀, lati ma rin ninu gbogbo ọ̀na rẹ̀, ati lati pa ofin rẹ̀ mọ́, ati aṣẹ rẹ̀, ati idajọ rẹ̀, ti o ti paṣẹ fun awọn baba wa.

59. Ki o si jẹ ki ọ̀rọ mi wọnyi, ti mo fi bẹ̀bẹ niwaju Oluwa, ki o wà nitosi, Oluwa Ọlọrun wa, li ọsan ati li oru, ki o le mu ọ̀ran iranṣẹ rẹ duro, ati ọ̀ran ojojumọ ti Israeli, enia rẹ̀.

60. Ki gbogbo enia aiye le mọ̀ pe, Oluwa on li Ọlọrun, kò si ẹlomiran.

61. Nitorina, ẹ jẹ ki aìya nyin ki o pé pẹlu Oluwa Ọlọrun wa, lati mã rìn ninu aṣẹ rẹ̀, ati lati pa ofin rẹ̀ mọ́, bi ti oni yi.

62. Ati ọba, ati gbogbo Israeli pẹlu rẹ̀, ru ẹbọ niwaju Oluwa.