Yorùbá Bibeli

Luk 1:40-57 Yorùbá Bibeli (YCE)

40. O si wọ̀ ile Sakariah lọ o si ki Elisabeti.

41. O si ṣe, nigbati Elisabeti gbọ́ kikí Maria, ọlẹ̀ sọ ninu rẹ̀; Elisabeti si kún fun Ẹmí Mimọ́:

42. O si ke li ohùn rara, o si wipe, Alabukun-fun ni iwọ ninu awọn obinrin, alabukun-fun si ni fun ọmọ inu rẹ.

43. Nibo si li eyi ti wá ba mi, ti iya Oluwa mi iba fi tọ̀ mi wá?

44. Sawò o, bi ohùn kikí rẹ ti bọ́ si mi li etí, ọlẹ̀ sọ ninu mi fun ayọ̀.

45. Alabukun-fun si li ẹniti o gbagbọ́: nitori nkan wọnyi ti a ti sọ fun u lati ọdọ Oluwa wá yio ṣẹ.

46. Maria si dahùn, o ni, Ọkàn mi yìn Oluwa logo,

47. Ẹmí mi si yọ̀ si Ọlọrun Olugbala mi.

48. Nitoriti o ṣijuwò ìwa irẹlẹ ọmọbinrin ọdọ rẹ̀: sá wò o, lati isisiyi lọ gbogbo iran enia ni yio ma pè mi li alabukunfun.

49. Nitori ẹniti o li agbara ti ṣe ohun ti o tobi fun mi; mimọ́ si li orukọ rẹ̀.

50. Anu rẹ̀ si mbẹ fun awọn ti o bẹ̀ru rẹ̀ lati irandiran.

51. O ti fi agbara hàn li apa rẹ̀; o ti tú awọn onirera ká ni ironu ọkàn wọn.

52. O ti mu awọn alagbara kuro lori itẹ́ wọn, o si gbé awọn talakà leke.

53. O ti fi ohun ti o dara kún awọn ti ebi npa; o si rán awọn ọlọrọ̀ pada lọwọ ofo.

54. O ti ràn Israeli ọmọ-ọdọ rẹ̀ lọwọ, ni iranti ãnu rẹ̀;

55. Bi o ti sọ fun awọn baba wa, fun Abrahamu, ati fun irú-ọmọ rẹ̀ lailai.

56. Maria si ba a joko niwọn oṣù mẹta, o si pada lọ si ile rẹ̀.

57. Ọjọ Elisabeti pe wayi ti yio bí; o si bí ọmọkunrin kan.