Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 18:35-37 Yorùbá Bibeli (YCE)

35. Tani ninu gbogbo awọn oriṣa ilẹ wọnni ti o gbà ilẹ wọn kuro lọwọ mi, ti Oluwa yio fi gbà Jerusalemu kuro lọwọ mi?

36. Ṣugbọn awọn enia pa ẹnu wọn mọ́, nwọn kò si da a li ohun ọ̀rọ kan: nitori aṣẹ ọba ni, pe, Ẹ máṣe da a li ohùn.

37. Nigbana ni Eliakimu ọmọ Hilkiah ti iṣe olori ile, ati Ṣebna akọwe, ati Joa ọmọ Asafu akọwe-iranti wá sọdọ Hesekiah, ti awọn, ti aṣọ wọn ni fifàya, nwọn si sọ ọ̀rọ Rabṣake fun u.