Yorùbá Bibeli

1. A. Ọba 11:23-26 Yorùbá Bibeli (YCE)

23. Pẹlupẹlu Ọlọrun gbe ọta dide si i; ani Resoni, ọmọ Eliada, ti o ti sá kuro lọdọ Hadadeseri oluwa rẹ̀, ọba Soba:

24. On si ko enia jọ sọdọ ara rẹ̀, o si di olori-ogun ẹgbẹ́ kan, nigbati Dafidi fi pa wọn, nwọn si lọ si Damasku, nwọn ngbe ibẹ, nwọn si jọba ni Damasku.

25. On si ṣe ọta si Israeli ni gbogbo ọjọ Solomoni, lẹhin ibi ti Hadadi ṣe: Resoni si korira Israeli, o si jọba lori Siria.

26. Ati Jeroboamu, ọmọ Nebati, ara Efrati ti Sereda, iranṣẹ Solomoni, orukọ iya ẹniti ijẹ Serua, obinrin opó kan, on pẹlu gbe ọwọ soke si ọba.