Yorùbá Bibeli

Ẹk. Jer 4:5-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Awọn ti o ti njẹ ohun didùndidùn nkú lọ ni ita: awọn ti a ti tọ́ ninu aṣọ-òdodó, gbá ãtàn mọra.

6. Nitori aiṣedede ọmọbinrin awọn enia mi tobi jù ẹ̀ṣẹ Sodomu lọ, ti a bì ṣubu ni iṣẹju, laisi iṣiṣẹ ọwọ ninu rẹ̀.

7. Awọn Nasire rẹ̀ mọ́ jù ẹ̀gbọn-owu, nwọn funfun jù wàra; irisi wọn pọn jù iyùn, apẹrẹ wọn dabi okuta Safire:

8. Oju wọn dudu jù ẽdu nisisiyi; a kò mọ̀ wọn ni ita: àwọ wọn lẹ mọ egungun wọn; o di gbigbẹ gẹgẹ bi igi.

9. Awọn ti a fi idà pa san jù awọn ti a fi ebi pa, ti ndaku, ti a gún wọn lara nitori aisi eso-oko.

10. Ọwọ awọn obinrin alãnu ti sè awọn ọmọ awọn tikarawọn: awọn wọnyi li ohun jijẹ fun wọn ni igba wahala ọmọbinrin awọn enia mi.

11. Oluwa ti ṣe aṣepe irunu rẹ̀; o ti dà ibinu gbigbona rẹ̀ jade, o ti dá iná ni Sioni, ti o si ti jo ipilẹ rẹ̀ run.