Yorùbá Bibeli

O. Daf 97:3-8 Yorùbá Bibeli (YCE)

3. Iná ṣaju rẹ̀, o si jo awọn ọta rẹ̀ yika kiri.

4. Manamana rẹ̀ kọ imọlẹ si aiye: aiye ri i, o si wariri.

5. Awọn òke nyọ́ bi ida niwaju Oluwa, niwaju Oluwa gbogbo aiye:

6. Ọrun fi ododo rẹ̀ hàn, gbogbo orilẹ-ède si ri ogo rẹ̀.

7. Oju yio tì gbogbo awọn ti nsìn ere fifin, ẹniti nfi ere ṣe ileri ara wọn: ẹ ma sìn i, gbogbo ẹnyin ọlọrun.

8. Sioni gbọ́, inu rẹ̀ si dùn; awọn ọmọbinrin Juda si yọ̀, Oluwa, nitori idajọ rẹ.