Yorùbá Bibeli

O. Daf 68:29-32 Yorùbá Bibeli (YCE)

29. Nitori tempili rẹ ni Jerusalemu li awọn ọba yio ma mu ọrẹ fun ọ wá.

30. Ba awọn ẹranko ẽsu wi, ọ̀pọlọpọ awọn akọ-malu, pẹlu awọn ọmọ-malu enia, titi olukulùku yio fi foribalẹ pẹlu ìwọn fadaka: tú awọn enia ti nṣe inu didùn si ogun ka.

31. Awọn ọmọ-alade yio ti Egipti jade wá; nisisiyi ni Etiopia yio nà ọwọ rẹ̀ si Ọlọrun.

32. Ẹ kọrin si Ọlọrun, ẹnyin ijọba aiye; ẹ kọrin iyìn si Oluwa.