Yorùbá Bibeli

O. Daf 66:6-18 Yorùbá Bibeli (YCE)

6. O sọ okun di ilẹ gbigbẹ: nwọn fi ẹsẹ là odò já: nibẹ li awa gbe yọ̀ ninu rẹ̀.

7. O jọba nipa agbara rẹ̀ lailai; oju rẹ̀ nwò awọn orilẹ-ède: ki awọn ọlọtẹ ki o máṣe gbé ara wọn ga.

8. Ẹ fi ibukún fun Ọlọrun wa, ẹnyin enia, ki ẹ si mu ni gbọ́ ohùn iyìn rẹ̀.

9. Ẹniti o mu ẹmi wa wà lãye, ti kò si jẹ ki ẹsẹ wa ki o yẹ̀.

10. Ọlọrun, nitori ti iwọ ti ridi wa: iwọ ti dan wa wò, bi ã ti idan fadaka wò.

11. Iwọ mu wa wọ̀ inu àwọn; iwọ fi ipọnju le wa li ẹgbẹ.

12. Iwọ mu awọn enia gùn wa li ori: awa nwọ inu iná ati omi lọ, ṣugbọn iwọ mu wa jade wá si ibi irọra.

13. Emi o lọ sinu ile rẹ ti emi ti ẹbọ sisun: emi o san ẹjẹ́ mi fun ọ,

14. Ti ète mi ti jẹ́, ti ẹnu si ti sọ, nigbati mo wà ninu ipọnju.

15. Emi o ru ẹbọ sisun ọlọra si ọ, pẹlu õrùn ọrá àgbo; emi o rubọ akọ-malu pẹlu ewurẹ.

16. Ẹ wá gbọ́, gbogbo ẹnyin ti o bẹ̀ru Ọlọrun, emi o sọ ohun ti o ṣe fun ọkàn mi.

17. Emi fi ẹnu mi kigbe pè e, emi o si fi àhọn mi buyin fun u.

18. Bi emi ba gbà ẹ̀ṣẹ li aiya mi, Oluwa kì yio gbohùn mi: