Yorùbá Bibeli

O. Daf 48:3-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

3. A mọ̀ Ọlọrun li àbo ninu ãfin rẹ̀.

4. Sa wò o, awọn ọba pejọ pọ̀, nwọn jumọ nkọja lọ.

5. Nwọn ri i, bẹ̃li ẹnu yà wọn; a yọ wọn lẹnu, nwọn yara lọ.

6. Ẹ̀ru bà wọn nibẹ, ati irora bi obinrin ti nrọbi.

7. Iwọ fi ẹfufu ila-õrun fọ́ ọkọ Tarṣiṣi.

8. Bi awa ti gbọ́, bẹ̃li awa ri ni ilu Oluwa awọn ọmọ-ogun, ni ilu Ọlọrun wa: Ọlọrun yio gbé e kalẹ lailai.

9. Awa ti nrò ti iṣeun-ifẹ rẹ, Ọlọrun, li arin tempili rẹ.

10. Ọlọrun, gẹgẹ bi orukọ rẹ, bẹ̃ni iyìn rẹ de opin aiye: ọwọ ọtún rẹ kún fun ododo.

11. Ki òke Sioni ki o yọ̀, ki inu awọn ọmọbinrin Juda ki o dùn, nitori idajọ rẹ.