Yorùbá Bibeli

O. Daf 35:22-28 Yorùbá Bibeli (YCE)

22. Eyi ni iwọ ti ri, Oluwa: máṣe dakẹ: Oluwa máṣe jina si mi.

23. Rú ara rẹ soke, ki o si ji si idajọ mi, ati si ọ̀ran mi, Ọlọrun mi ati Oluwa mi.

24. Ṣe idajọ mi, Oluwa Ọlọrun mi, gẹgẹ bi ododo rẹ, ki o má si ṣe jẹ ki nwọn ki o yọ̀ mi.

25. Máṣe jẹ ki nwọn kí o wi ninu ọkàn wọn pe, A! bẹ̃li awa nfẹ ẹ: máṣe jẹ ki nwọn ki o wipe, Awa ti gbé e mì.

26. Ki oju ki o tì wọn, ki nwọn ki o si dãmu pọ̀, ti nyọ̀ si ifarapa mi: ki a fi itiju ati àbuku wọ̀ wọn ni aṣọ, ti ngberaga si mi.

27. Jẹ ki nwọn ki o ma hó fun ayọ̀, ki nwọn ki o si ma ṣe inu-didùn, ti nṣe oju-rere si ododo mi: lõtọ ki nwọn ki o ma wi titi pe, Oluwa ni ki a ma gbega, ti o ni inu-didùn si alafia iranṣẹ rẹ̀.

28. Ahọn mi yio si ma sọ̀rọ ododo rẹ, ati ti iyìn rẹ ni gbogbo ọjọ.