Yorùbá Bibeli

O. Daf 35:14-20 Yorùbá Bibeli (YCE)

14. Emi ṣe ara mi bi ẹnipe ọrẹ tabi arakunrin mi tilẹ ni: emi fi ibinujẹ tẹriba, bi ẹniti nṣọ̀fọ iya rẹ̀.

15. Ṣugbọn ninu ipọnju mi nwọn yọ̀, nwọn si kó ara wọn jọ: awọn enia-kenia kó ara wọn jọ si mi, emi kò si mọ̀; nwọn fa mi ya, nwọn kò si dakẹ.

16. Pẹlu awọn àgabagebe ti iṣe ẹlẹya li apejẹ, nwọn npa ehin wọn si mi.

17. Oluwa iwọ o ti ma wò pẹ to? yọ ọkàn mi kuro ninu iparun wọn, ẹni mi kanna lọwọ awọn kiniun.

18. Emi o ṣọpẹ fun ọ ninu ajọ nla: emi o ma yìn ọ li awujọ ọ̀pọ enia.

19. Máṣe jẹ ki awọn ti nṣe ọta mi lodi ki o yọ̀ mi; bẹ̃ni ki o má si ṣe jẹ ki awọn ti o korira mi li ainidi ki o ma ṣẹju si mi.

20. Nitori ti nwọn kò sọ̀rọ alafia: ṣugbọn nwọn humọ ọ̀ran ẹ̀tan si awọn enia jẹjẹ ilẹ na.