Yorùbá Bibeli

O. Daf 28:5-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Nitori ti nwọn kò kà iṣẹ Oluwa si, tabi iṣẹ ọwọ rẹ̀; on o run wọn, kì yio si gbé wọn ró.

6. Olubukún ni Oluwa, nitoriti o ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ mi.

7. Oluwa li agbara ati asà mi; on li aiya mi gbẹkẹle, a si nràn mi lọwọ: nitorina inu mi dùn jọjọ: emi o si ma fi orin mi yìn i.

8. Oluwa li agbara wọn, on si li agbara igbala ẹni-ororo rẹ̀.

9. Gbà awọn enia rẹ là, ki o si busi ilẹ-ini rẹ: ma bọ́ wọn pẹlu, ki o si ma gbé wọn leke lailai.