Yorùbá Bibeli

O. Daf 121:4-8 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Kiyesi i, ẹniti npa Israeli mọ́, kì itõgbe, bẹ̃ni kì isùn.

5. Oluwa li olupamọ́ rẹ: Oluwa li ojiji rẹ li ọwọ ọ̀tún rẹ.

6. Orùn kì yio pa ọ nigba ọsan, tabi oṣupa nigba oru.

7. Oluwa yio pa ọ mọ́ kuro ninu ibi gbogbo: yio pa ọkàn rẹ mọ́.

8. Oluwa yio pa alọ ati àbọ rẹ mọ́ lati igba yi lọ, ati titi lailai.