Yorùbá Bibeli

O. Daf 118:8-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

8. O ya lati gbẹkẹle Oluwa, jù ati gbẹkẹle enia lọ.

9. O ya lati gbẹkẹle Oluwa, jù ati gbẹkẹle awọn ọmọ-alade lọ.

10. Gbogbo awọn orilẹ-ède yi mi ka kiri, ṣugbọn li orukọ Oluwa emi o pa wọn run.

11. Nwọn yi mi ka kiri; nitõtọ, nwọn yi mi ka kiri, ṣugbọn li orukọ Oluwa emi o pa wọn run.

12. Nwọn yi mi ka kiri bi oyin; a si pa wọn bi iná ẹgún: li orukọ Oluwa emi o sa pa wọn run.

13. Iwọ tì mi gidigidi ki emi ki o le ṣubu; ṣugbọn Oluwa ràn mi lọwọ.

14. Oluwa li agbara ati orin mi, o si di igbala mi.

15. Ìró ayọ̀ ati ti ìṣẹ́gun mbẹ ninu agọ awọn olododo; ọwọ ọtún Oluwa li a gbega: ọwọ ọtún Oluwa nṣe agbara.

16. Ọwọ ọtún Oluwa li a gbega: ọwọ ọtún Oluwa nṣe agbara.

17. Emi kì yio kú, bikoṣe yiyè, ki emi ki o si ma rohin iṣẹ Oluwa.

18. Oluwa nà mi gidigidi: ṣugbọn kò fi mi fun ikú.

19. Ṣi ilẹkun ẹnu-ọ̀na ododo silẹ fun mi: emi o ba ibẹ wọle, emi o ma yìn Oluwa.

20. Eyi li ẹnu-ọ̀na Oluwa, ti awọn olododo yio ba wọle.

21. Emi o yìn ọ: nitori ti iwọ gbohùn mi, iwọ si di igbala mi.