Yorùbá Bibeli

O. Daf 118:16-23 Yorùbá Bibeli (YCE)

16. Ọwọ ọtún Oluwa li a gbega: ọwọ ọtún Oluwa nṣe agbara.

17. Emi kì yio kú, bikoṣe yiyè, ki emi ki o si ma rohin iṣẹ Oluwa.

18. Oluwa nà mi gidigidi: ṣugbọn kò fi mi fun ikú.

19. Ṣi ilẹkun ẹnu-ọ̀na ododo silẹ fun mi: emi o ba ibẹ wọle, emi o ma yìn Oluwa.

20. Eyi li ẹnu-ọ̀na Oluwa, ti awọn olododo yio ba wọle.

21. Emi o yìn ọ: nitori ti iwọ gbohùn mi, iwọ si di igbala mi.

22. Okuta ti awọn ọ̀mọle kọ̀ silẹ li o di pataki igun ile.

23. Lati ọdọ Oluwa li eyi: o ṣe iyanu li oju wa.