Yorùbá Bibeli

O. Daf 118:1-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. Ẹ fi ọpẹ fun Oluwa; nitoriti o ṣeun, nitoriti ãnu rẹ̀ duro lailai.

2. Jẹ ki Israeli ki o wi nisisiyi pe, ãnu rẹ̀ duro lailai.

3. Jẹ ki ara-ile Aaroni ki o wi nisisiyi pe, ãnu rẹ̀ duro lailai.

4. Jẹ ki awọn ti o bẹ̀ru Oluwa ki o wi nisisiyi pe, ãnu rẹ̀ duro lailai.

5. Mo kepè Oluwa ninu ipọnju: Oluwa si da mi lohùn ni ibi àye nla.

6. Oluwa mbẹ fun mi, emi kì yio bẹ̀ru; kili enia le ṣe si mi?

7. Oluwa mbẹ fun mi pẹlu awọn ti nràn mi lọwọ: nitorina li emi o ṣe ri ifẹ mi lori awọn ti o korira mi.

8. O ya lati gbẹkẹle Oluwa, jù ati gbẹkẹle enia lọ.

9. O ya lati gbẹkẹle Oluwa, jù ati gbẹkẹle awọn ọmọ-alade lọ.