Yorùbá Bibeli

Luk 19:17-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. O si wi fun u pe, O ṣeun, iwọ ọmọ-ọdọ rere: nitoriti iwọ ṣe olõtọ li ohun kikini, gbà aṣẹ lori ilu mẹwa.

18. Eyi ekeji si wá, o wipe, Oluwa, mina rẹ jère mina marun.

19. O si wi fun u pẹlu pe, Iwọ joye ilu marun.

20. Omiran si wá, o wipe, Oluwa, wò mina rẹ ti mbẹ li ọwọ́ mi ti mo dì sinu gèle:

21. Nitori mo bẹ̀ru rẹ, ati nitoriti iwọ ṣe onrorò enia: iwọ a ma mu eyi ti iwọ ko fi lelẹ, iwọ a si ma ká eyi ti iwọ kò gbìn.