Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 3:1-4 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. JEHORAMU, ọmọ Ahabu si bẹ̀rẹ si ijọba lori Israeli ni Samaria li ọdun kejidilogun Jehoṣafati, ọba Juda, o si jọba li ọdun mejila.

2. O si ṣe buburu li oju Oluwa; ṣugbọn kì iṣe bi baba rẹ̀, ati bi iya rẹ̀: nitoriti o mu ere Baali ti baba rẹ̀ ti ṣe kuro.

3. Ṣugbọn o fi ara mọ ẹ̀ṣẹ Jeroboamu, ọmọ Nebati, ti o mu Israeli dẹ̀ṣẹ; kò si lọ kuro ninu rẹ̀.

4. Meṣa, ọba Moabu si nsìn agutan, o si nsan ọkẹ marun ọdọ-agutan, ati ọkẹ marun àgbo irun fun ọba Israeli.