Yorùbá Bibeli

2. A. Ọba 20:4-13 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. O si ṣe, ki Isaiah ki o to jade si ãrin agbalá-ãfin, li ọ̀rọ Oluwa tọ̀ ọ wá wipe,

5. Tun pada, ki o si wi fun Hesekiah olori awọn enia mi pe, Bayi li Oluwa Ọlọrun Dafidi baba rẹ wi pe, Emi ti gbọ́ adura rẹ, emi si ti ri omije rẹ: kiyesi i, emi o wò ọ sàn: ni ijọ kẹta iwọ o gòke lọ si ile Oluwa.

6. Emi o si bù ọdun mẹ̃dogun kún ọjọ rẹ: emi o si gbà ọ ati ilu yi lọwọ ọba Assiria, emi o si dãbò bò ilu yi, nitori ti emi tikara mi, ati nitori ti Dafidi iranṣẹ mi.

7. Isaiah si wipe, Mu odidi ọ̀pọtọ. Nwọn si mu u, nwọn si fi le õwo na, ara rẹ̀ si da.

8. Hesekiah si wi fun Isaiah pe, Kini yio ṣe àmi pe Oluwa yio wò mi sàn, ati pe emi o gòke lọ si ile Oluwa ni ijọ kẹta?

9. Isaiah si wipe, Àmi yi ni iwọ o ni lati ọdọ Oluwa wá, pe, Oluwa yio ṣe nkan yi ti on ti sọ: ki ojiji ki o lọ siwaju ni iṣisẹ̀ mẹwa ni, tabi ki o pada sẹhin ni iṣisẹ̀ mẹwa?

10. Hesekiah si dahùn wipe, Ohun ti o rọrùn ni fun ojiji ki o lọ siwaju ni iṣisẹ̀ mẹwa: bẹ̃kọ, ṣugbọn jẹ ki ojiji ki o pada sẹhin ni iṣisẹ̀ mẹwa.

11. Isaiah woli si kepè Oluwa; on si mu ojiji pada sẹhin ni iṣisẹ̀ mẹwa, nipa eyiti o ti sọ̀kalẹ ninu agogo-õrùn Ahasi.

12. Li akokò na ni Berodaki-Baladani, ọmọ Baladani, ọba Babeli, rán iwe ati ọrẹ si Hesekiah: nitoriti o ti gbọ́ pe Hesekiah ti ṣe aisàn.

13. Hesekiah si fi eti si ti wọn, o si fi gbogbo ile iṣura ohun iyebiye rẹ̀ hàn wọn, fadakà, ati wura, ati turari, ati ororo iyebiye, ati gbogbo ile ohun ihamọra rẹ̀, ati gbogbo eyiti a ri ninu iṣura rẹ̀: kò si nkan ni ile rẹ̀, tabi ni gbogbo ijọba rẹ̀, ti Hesekiah kò fi hàn wọn.