Yorùbá Bibeli

1. A. Ọba 15:26-33 Yorùbá Bibeli (YCE)

26. O si ṣe buburu niwaju Oluwa, o si rìn li ọ̀na baba rẹ̀, ati ninu ẹ̀ṣẹ rẹ̀ eyiti o mu Israeli ṣẹ̀.

27. Baaṣa ọmọ Ahijah ti ile Issakari, si dìtẹ si i; Baaṣa kọlu u ni Gibbetoni ti awọn ara Filistia: nitori Nadabu ati gbogbo Israeli dó ti Gibbetoni.

28. Ani li ọdun kẹta ti Asa ọba Juda, ni Baaṣa pa a, o si jọba ni ipò rẹ̀.

29. O si ṣe, nigbati o jọba, o kọlu gbogbo ile Jeroboamu; kò kù fun Jeroboamu ẹniti nmí, titi o fi run u, gẹgẹ bi ọ̀rọ Ọluwa, ti o sọ nipa ọwọ́ iranṣẹ rẹ̀, Ahijah ara Ṣilo:

30. Nitori ẹ̀ṣẹ Jeroboamu ti o ṣẹ̀, ti o si mu ki Israeli ṣẹ̀, nipa imunibinu rẹ̀, eyiti o fi mu ki Oluwa Ọlọrun Israeli ki o binu.

31. Ati iyokù iṣe Nadabu, ati gbogbo ohun ti o ṣe, a kò ha kọ wọn sinu iwe ọ̀rọ ọjọ awọn ọba Israeli.

32. Ogun si wà, lãrin Asa ati Baaṣa ọba Israeli ni gbogbo ọjọ wọn.

33. Li ọdun kẹta Asa, ọba Juda, ni Baaṣa, ọmọ Ahijah bẹ̀rẹ si ijọba lori gbogbo Israeli ni Tirsa, li ọdun mẹrinlelogun.