Yorùbá Bibeli

Hag 1:7-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

7. Bayi li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi: Ẹ kiyesi ọ̀na nyin.

8. Ẹ gùn ori oke-nla lọ, ẹ si mu igi wá, ki ẹ si kọ́ ile na; inu mi yio si dùn si i, a o si yìn mi logo, li Oluwa wi.

9. Ẹnyin tí nreti ọ̀pọ, ṣugbọn kiyesi i, diẹ ni; nigbati ẹnyin si mu u wá ile, mo si fẹ ẹ danù. Nitori kini? li Oluwa awọn ọmọ-ogun wi. Nitori ti ile mi ti o dahoro; ti olukuluku nyin si nsare fun ile ara rẹ̀.

10. Nitorina ni a ṣe dá ìri ọrun duro lori nyin, a si da eso ilẹ duro.

11. Mo si ti pè ọdá sori ilẹ, ati sori oke-nla, ati sori ọkà ati sori ọti-waini titún, ati sori ororo, ati sori ohun ti ilẹ mu jade, ati sori enia, ati sori ẹran, ati sori gbogbo iṣẹ ọwọ ẹni.

12. Nigbana ni Serubbabeli ọmọ Ṣealtieli, ati Joṣua ọmọ Josedeki, olori alufa, pẹlu gbogbo enia iyokù, gba ohùn Oluwa Ọlọrun wọn gbọ́, ati ọ̀rọ Hagai woli, gẹgẹ bi Oluwa Ọlọrun wọn ti rán a, awọn enia si bẹ̀ru niwaju Oluwa.