Yorùbá Bibeli

Esr 9:10-15 Yorùbá Bibeli (YCE)

10. Njẹ nisisiyi, Ọlọrun wa, kili awa o wi lẹhin eyi? nitoriti awa ti kọ̀ aṣẹ rẹ silẹ,

11. Ti iwọ ti pa lati ẹnu awọn woli iranṣẹ rẹ wá, wipe, Ilẹ na ti ẹnyin nlọ igbà nì, ilẹ alaimọ́ ni, fun ẹgbin awọn enia ilẹ na, fun irira wọn, pẹlu ìwa-ẽri ti nwọn fi kun lati ikangun kan de ekeji.

12. Njẹ nitorina ki ẹnyin ki o máṣe fi ọmọ nyin obinrin fun ọmọ wọn ọkunrin, bẹ̃ni ki ẹnyin ki o máṣe mu ọmọ wọn obinrin fun ọmọ nyin ọkunrin, bẹ̃ni ki ẹnyin ki o máṣe wá alafia wọn tabi irọra wọn titi lai: ki ẹnyin ki o le ni agbara, ki ẹ si le ma jẹ ire ilẹ na, ki ẹ si le fi i silẹ fun awọn ọmọ nyin ni ini titi lai.

13. Ati lẹhin gbogbo eyi ti o de si wa nitori iṣe buburu wa, ati nitori ẹbi wa nla, nitoripe iwọ Ọlọrun wa ti dá wa si ju bi o ti yẹ lọ fun aiṣedede wa, o si fi iru igbala bi eyi fun wa;

14. Awa iba ha tun ru ofin rẹ? ki awa ki o si ma ba awọn enia irira wọnyi dá ana? iwọ kì o ha binu si wa titi iwọ o fi pa wa run tan, tobẹ̃ ti ẹnikan kò si ni kù, tabi ẹnikan ti o sala?

15. Olododo ni iwọ Oluwa Ọlọrun Israeli: awa ni iyokù ati asala gẹgẹ bi o ti ri li oni yi: wò o, awa duro niwaju rẹ ninu ẹbi wa, nitoripe awa ki o le duro niwaju rẹ nitori eyi.