Yorùbá Bibeli

Esr 2:4-19 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Awọn ọmọ Ṣefatiah, irinwo o din mejidilọgbọn.

5. Awọn ọmọ Ara, ẹgbẹrin o din mẹ̃dọgbọn.

6. Awọn ọmọ Pahati-Moabu ninu awọn ọmọ Jeṣua, ati Joabu, ẹgbẹrinla o le mejila.

7. Awọn ọmọ Elamu, adọtalelẹgbẹfa o le mẹrin.

8. Awọn ọmọ Sattu, ọtadilẹgbẹ̀run, o le marun.

9. Awọn ọmọ Sakkai, ojidilẹgbẹrin.

10. Awọn ọmọ Bani, ojilelẹgbẹta, o le meji.

11. Awọn ọmọ Bebai, ẹgbẹta o le mẹtalelogun.

12. Awọn ọmọ Asgadi, ẹgbẹfa, o le mejilelogun.

13. Awọn ọmọ Adonikami ọtalelẹgbẹta o le mẹfa.

14. Awọn ọmọ Bigfai, ẹgbã o le mẹrindilọgọta.

15. Awọn ọmọ Adini, adọtalenirinwo o le mẹrin.

16. Awọn ọmọ Ateri ti Hesekiah, mejidilọgọrun.

17. Awọn ọmọ Besai, ọrindinirinwo o le mẹta.

18. Awọn ọmọ Jora, mejilelãdọfa.

19. Awọn ọmọ Haṣumu igba o le mẹtalelogun.