Yorùbá Bibeli

Esr 2:1-7 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. WỌNYI li awọn ọmọ igberiko Juda ti o goke wa, lati inu igbèkun awọn ti a ti ko lọ, ti Nebukadnessari, ọba Babiloni, ti ko lọ si Babiloni, ti nwọn si pada wá si Jerusalemu ati Juda, olukuluku si ilu rẹ̀:

2. Awọn ti o ba Serubbabeli wá, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu, Baana. Iye awọn ọkunrin ninu awọn enia Israeli:

3. Awọn ọmọ Paroṣi, ẹgbọkanla o din mejidilọgbọn.

4. Awọn ọmọ Ṣefatiah, irinwo o din mejidilọgbọn.

5. Awọn ọmọ Ara, ẹgbẹrin o din mẹ̃dọgbọn.

6. Awọn ọmọ Pahati-Moabu ninu awọn ọmọ Jeṣua, ati Joabu, ẹgbẹrinla o le mejila.

7. Awọn ọmọ Elamu, adọtalelẹgbẹfa o le mẹrin.