Yorùbá Bibeli

Ẹk. Jer 4:17-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

17. Bi o ṣe ti wa ni, oju wa nwọ̀na siwaju ati siwaju, fun iranlọwọ wa ti o jẹ asan: lori ile-iṣọ wa, awa nwọ̀na fun orilẹ-ède, ti kò le ràn ni lọwọ.

18. Nwọn dẹkun si ipa ọ̀na wa, ti awa kò le rìn ita wa: opin wa sunmọ tosi, ọjọ wa pé; nitori opin wa de.

19. Awọn ti nlepa wa yara jù idì ọrun lọ: nwọn nlepa wa lori oke wọnni, nwọn bà dè wa li aginju.

20. Ẽmi iho imu wa, ani ẹni-ororo Oluwa, ni a mu ninu ọ̀fin wọn, niti ẹniti awa wipe, labẹ ojiji rẹ̀ li awa o ma gbé lãrin awọn orilẹ-ède.

21. Yọ̀, ki inu rẹ si dùn, iwọ ọmọbinrin Edomu, ti ngbe inu ilẹ Usi; sibẹ ago na yio kọja sọdọ rẹ pẹlu: iwọ o si yo bi ọ̀muti, a o si tu ọ ni ihoho.